27. Ábúráhámù sì mú àgùntàn àti màlúù wá, ó sì kó wọn fún Ábímélékì. Àwọn méjèèjì sì dá májẹ̀mú.
28. Ábúráhámù sì ya abo ọ̀dọ́-àgùtàn méje nínú agbo àgùntàn rẹ̀ sọ́tọ̀.
29. Ábímélékì sì béèrè lọ́wọ́ Ábúráhámù pé, “Kín ni ìtumọ̀ yíyà tí ìwọ ya àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn méje wọ̀nyí sọ́tọ̀ sí.”
30. Ó da lóhùn pé “Gba àwọn abo ọ̀dọ́-àgùtàn méje wọ̀nyí lọ́wọ́ mi gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé èmi ni mo gbẹ́ kànga yìí.”
31. Nítorí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ náà ni Baa-Ṣébà nítorí níbẹ̀ ni àwọn méjèèjì gbé búra.
32. Lẹ́yìn májẹ̀mú tí wọ́n dá ní Báá-Ṣébà yìí ni Ábímélékì àti Píkólì olórí ogun rẹ̀ pada sí ilẹ̀ àwọn ará Fílístínì.
33. Ábúráhámù sì gbin igi Támárísíkì kan sí Báá-Ṣébà, níbẹ̀ ni ó sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run ayérayé.
34. Ábúráhámù sì gbé ilẹ̀ àwọn ará Fílístínì fún ọjọ́ pípẹ́.