Sáàmù 46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọlọ́run Dáàbò Bo Ìlú Àti Ènìyàn Rẹ̀

1. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára waó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ nínú ìgbà ìpọ́njú.

2. Nítori náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ sí ayé ní ìdítí òkè sì ṣubú sínú òkun

3. Tí omi Rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mìtí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára Rẹ̀. Sela

4. Odò ńlá kan wà tí sísàn Rẹ̀ mú ìnú ìlú Ọlọ́run dùnibi mímọ́, nibi ti ọ̀gá ògo ń gbé.

5. Ọlọ́run wà pẹ̀lú Rẹ̀, kò ní yẹ̀:Ọlọ́run yóò ràn an lọ́wọ́ ní kùtùkùtù ọ̀wúrọ̀

6. Àwọn orílẹ̀ èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba subúó gbé ohun Rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.

7. Ọlọ́run awọn ọmọ ogún wà pẹ̀lú waỌlọ́run Jákọ́bù ni ààbò wa

8. Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwairú ahoro tí ó ṣe ní ayé

9. O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayéó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjìó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná

10. Ẹ dúró jẹ́ẹ kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́runA ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀ èdèA o gbé mi ga ní ayé.

11. Ọlọ́run alágbára wà pẹ̀lú waỌlọ́run Jákọ́bù sì ni ààbò wa.