28. Kí Olúwa kí ó fún ọ ní ìrì ọ̀runàti nínú ọ̀rá ilẹ̀àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti wáìnì túntún.
29. Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́,kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ,máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ,kí àwọn ìyekan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọÈgún ni fún gbogbo ẹni tí ń fi ọ́ ré,Ìbùkún ni fún gbogbo ẹni tí ó súre fún ọ.”
30. Bí Ísáákì ti súre tan tí Jákọ́bù ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Ísọ̀ ti oko ọdẹ dé.
31. Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
32. Ìsáákì baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé “Èmi Ísọ̀, àkọ́bí rẹ ni.”
33. Nígbà náà ni Ísáákì wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un”
34. Nígbà tí Ísọ̀ gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sunkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
35. Ṣùgbọ́n Ísáákì wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ”
36. Ísọ̀ sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jákọ́bù, (Arẹ́nijẹ) bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsinyìí, ó tún gba ìbùkún mi! Áà! Baba mi, ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
37. Ísáákì sì dá Ísọ̀ lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún-un, àti oúnjẹ àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọpọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
38. Ísọ̀ sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi?, Ṣúre fún èmi náà, baba mi.” Ísọ̀ sì sunkún kíkankíkan.
39. Ísáákì bàbá rẹ̀ sì dá a lóhùn pé,“Ibùjòkòó rẹyóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀,àti sí ìrì ọ̀run láti òkè wá.
40. Nípa idà ni ìwọ yóò máa gbé,ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ,ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbáraìwọ yóò já àjàgà rẹ̀-kúrò lọ́rùn rẹìwọ yóò sì di òmìnira.”
41. Ísọ̀ sì kóríra Jákọ́bù nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi ṣáà ti fẹ́rẹ̀ẹ́ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jákọ́bù, arákùnrin mi.”
42. Nígbà tí Rèbékà sì gbọ́ ohun tí Ísọ̀ àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jákọ́bù, ó sì wí fun un pé, “Ísọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò àti pa ọ́.
43. Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ: Ṣá lọ sọ́dọ̀ Lábánì ẹ̀gbọ́n mi ní Háránì.