Léfítíkù 14:37-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Yóò yẹ àrùn náà wò, bí àrùn náà bá ti wà lára ògiri ilé náà nípa àmì àwọ̀ ewé tàbí àmì pupa tí ó sì jinlẹ̀, ju ara ògiri lọ.

38. Àlùfáà yóò jáde kúrò nínú ilé náà, yóò sì ti ilẹ̀kùn ilé náà pa fún ọjọ́ méje.

39. Àlùfáà yóò padà wá yẹ ilé náà wò ní ọjọ́ keje. Bí àrùn náà bá ti tàn ká ara ògiri.

40. Àlùfáà yóò pàṣẹ kí a yọ àwọn òkúta tí àrùn náà ti bàjẹ́ kúrò kí a sì kó wọn dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú.

41. Yóò sì mú kí wọ́n ha ògiri inú ilé náà yíká. Gbogbo ohun tí wọ́n fi rẹ́ ilé náà tí ó ti ha ni kí wọ́n kó dànù sí ibi tí a kà sí àìmọ́ lẹ́yìn ìlú náà.

42. Òkúta mìíràn ni kí wọ́n fi dípò àwọn tí a ti yọ dànù kí wọ́n sì rẹ́ ilé náà pẹ̀lú àwọn ohun ìrẹ́lé tuntun.

Léfítíkù 14