Jẹ́nẹ́sísì 5:17-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Àpapọ̀ iye ọdún rẹ̀ jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ̀gbẹ̀rún-ọdún-ó-dín-márùn-ún (895), ó sì kú.

18. Nígbà tí Járédì pé ọmọ ọgọ́jọ-ó-lé-méjì ọdún (162) ni ó bí Énọ́kù.

19. Lẹ́yìn èyí, ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún (800) ó sì bí àwọn ọmọkúnrin àti ọmọbìnrin.

20. Àpapọ̀ ọdún rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún-dín-méjìdínlógójì (962); ó sì kú.

21. Nígbà tí Énọ́kù pé ọmọ ọgọ́ta-ó-lé-márùn ọdún (65) ni ó bí Mètúsẹ́là.

22. Lẹ́yìn tí ó bí Mètúsẹ́là, Énọ́kù sì bá Ọlọ́run rìn ní ọ̀ọ́dúnrún ọdún (300), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.

23. Àpapọ̀ ọjọ́ Énọ́kù sì jẹ́ irínwó-dín-márùndínlógójì-ọdún (365).

24. Énọ́kù bá Ọlọ́run rìn: a kò sì rí i mọ́ nítorí Ọlọ́run mú un lọ.

25. Nígbà tí Mètúsẹ́là pé igba-ó-dín-mẹ́talá ọdún (187) ní o bí Lámékì.

26. Lẹ́yìn èyí ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin-dín-méjìdínlógún ọdún (782), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.

27. Àpapọ̀ ọdún Mètúsẹ́là jẹ́ ẹgbẹ̀rún-ọdún-ó-dín-mọ́kànlélọ́gbọ̀n (969), ó sì kú.

28. Nígbà tí Lámékì pé ọdún méjìlélọ́gọ́sàn án (182) ni ó bí ọmọkùnrin kan.

29. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Nóà, ó sì wí pé, “Eléyìí ni yóò tù wá nínú ni iṣẹ́ àti làálàá ọwọ́ wa, nítorí ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi gégùn-ún.”

Jẹ́nẹ́sísì 5