Ámósì 9:3-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Kámẹ́lì,èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìṣàlẹ̀ òkun,láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.

4. Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọnláti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,kì í sì í se fún rere.”

5. Olúwa, Ọlọ́run AlágbáraẸni ti ó fi ọwọ́ kan ìlẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì sọ̀fọ̀Gbogbo orílẹ̀ èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Náìlìti wọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Éjíbítì.

6. Òun ni ẹni tí ó kọ́ itẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀runti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayéẸni ti ó pe àwọn omi òkunti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

Ámósì 9