2 Kíróníkà 33:20-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Mánásè sinmi pẹ̀lú àwọn bàbá rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Ámónì ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba

21. Ámónì jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún méjì.

22. Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ Mánásè ti ṣe. Ámónì sìn ó sì rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà tí Mánásè ti ṣe.

23. Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba a rẹ̀ Mánásè. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: Ẹ̀bi Ámónì ń ga sí i.

24. Àwọn onísẹ́ Ámónì dìtẹ̀ síi. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀

25. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Ámónì, wọ́n sì mú Jósíà ọmọ rẹ̀ jọba ní ipò rẹ̀.

2 Kíróníkà 33