1 Ọba 14:10-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. “ ‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jéróbóámù. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jéróbóámù, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Ísírẹ́lì. Èmi yóò mú ilé Jéróbóámù kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.

11. Ajá yóò jẹ ẹni Jéróbóámù tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní ìgbẹ́ ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’

12. “Níti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.

13. Gbogbo Ísírẹ́lì yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jéróbóámù, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ní ilé Jéróbóámù.

14. “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fún ra rẹ̀ lórí Ísírẹ́lì tí yóò ké ilé Jéróbóámù kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsìnyìí.

15. Olúwa yóò kọlu Ísírẹ́lì, yóò sì dà bí a ti ń mi ìyẹ́ nínú omi. Yóò sì fa Ísírẹ́lì tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère òrìṣà.

16. Yóò sì kọ Ísírẹ́lì sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jéróbóámù ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Ísírẹ́lì ṣẹ̀.”

17. Nígbà náà ni aya Jéróbóámù sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tírà. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.

18. Wọ́n sì sin ín, gbogbo Ísírẹ́lì sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ábíjà wòlíì.

19. Ìyòókù ìṣe Jéróbóámù, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì.

20. Jéróbóámù sì jọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nádábù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

21. Réhóbóámù ọmọ Sólómónì sì jọba ní Júdà. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, ó sì jọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jérúsálẹ́mù, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Náámà, ará Ámónì.

22. Júdà sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.

1 Ọba 14