Sáàmù 59:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run;dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.

2. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburúkí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.

3. Wòó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí!Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí miKìí se nítorí ìrékọja mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.

4. Èmí kò ṣe àìṣedédé kan, ṣíbẹ̀ wọ́n sáré,wọ́n ṣetán láti kọlù mi. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi,kí o sì wo àìlera mi.

5. Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Ísírẹ́lì,dìde fún ara Rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀ èdè wí;Má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. Sela

Sáàmù 59