Sáàmù 44:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àti fi ètí wa gbọ́, Ọlọ́runàwọn baba wa tí sọ fún waoun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn,ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.

2. Ìwọ fi ọwọ́ Rẹ̀ lé orílẹ̀-èdè jádeÌwọ sì gbin àwọn baba wa;Ìwọ run àwọn ènìyàn náàÌwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.

3. Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọn gba ilẹ̀ náà,bẹ́ẹ̀ ni kì í se apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò se;ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ àti, apá Rẹ̀;àti ìmọ́lẹ̀ ojú Rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.

4. Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi,ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jákọ́bù.

5. Nípaṣẹ̀ Rẹ̀ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣúbú; nípasẹ̀ orúkọ Rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá ti ó dìde sí wa mọ́lẹ̀

6. Èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun miidà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,

Sáàmù 44