Òwe 21:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.

2. Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

3. Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nàó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

4. Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

5. Ètè àwọn olóye já sí èrèbí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

6. Ìṣúra tí a kójọ nípaṣẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹkùn ikú.

7. Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

8. Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

Òwe 21