23. “Kí ẹ̀yin yọ̀ ní ọjọ́ náà, kí ẹ̀yin sì fò sókè fún ayọ̀, nítorí tí ẹ̀yin ti gba ìtùnú yín ná.
24. “Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
25. Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó,nítorí ebi yóò pa yín,Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí,nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
26. Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere,nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn èké wòlíì.
27. “Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi: Ẹ fẹ́ àwọn ọ̀ta yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín;
28. Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
29. Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, pa èkejì dà sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù rẹ pẹ̀lú.
30. Sì fifún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ lẹ́rù, má sì ṣe padà bèèrè.
31. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
32. “Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kíni ẹ̀yin ní? Àwọn ‘ẹlẹ́ṣẹ̀’ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
33. Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kíni ẹ̀yin ní? Àwọn ‘ẹlẹ́sẹ̀’ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.