27. Ní Ríbílà ni ilẹ̀ Hámátì Ọba náà sì pa wọ́n. Báyìí ni Júdà sì sá kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
28. Èyí ni iye àwọn ènìyàn tí Nebukadinésárì kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì.Ní ọdún keje ẹgbẹ̀dógún ó lé mẹ́talélógún ará Júdà.
29. Ní ọdún kejìdínlógún Nebakadinésárìo kó ẹgbẹ̀rún ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n láti Jérúsálẹ́mù.
30. Ní ọdún kẹtàlélógún ènìyànJúù tí Nebukadinésárì kó lọ sí ilẹ̀ àjòjì jẹ́ márùn ún.Gbogbo ènìyàn tí ó kó lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀tàlélógún.
31. Ní ọdún kẹtàdín lógójì ti Jéhóáíkímù Ọba Júdà ni Efili-merodaki di Ọba Bábílónì. Ó tú Jéhóáíkímù Ọba Júdà sílẹ̀ nínú túbú ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n oṣù kéjìlá.
32. Ó ń sọ̀rọ̀ rere sí i, ó sì fún un ní ìjókòó ìgbéga, èyí tí ó ju ti àwọn Ọba yóòkù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Bábílónì.
33. Nítorí náà, Jéhóáíkímù bọ́ aṣọ ẹ̀wọ̀n rẹ̀ ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ fún ìyókù ọjọ́ ayé rẹ̀: Ó sì ń jẹun lórí àga Ọba.