Jeremáyà 51:27-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Gbé àṣíá sókè ní ilẹ̀ náà, fọnipe láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!Pèṣè àwọn orílẹ̀ èdè sílẹ̀ láti bá jagun,pe àwọn ìjọba yìí láti doju kọ ọ́,Árárátì, Mínínì àti Ásíkẹ́nì.Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,rán àwọn ẹṣin síi bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28. Pèsè àwọn orílẹ̀ èdè láti bá jagun,àwọn Ọba Médíà, Gómìnà àti gbogboọmọ ìgbìmọ̀ wọn àti gbogbo orílẹ̀ èdè tí wọ́n jọba lé lórí.

29. Ilẹ̀ wárìrì síhìn ín sọ́hùn ún, nítorí péète Olúwa, sí Bábílónì dúróláti ba ilẹ̀ Bábílónì jẹ́ lọ́nàtí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.

30. Gbogbo àwọn jagunjagunBábílónì tó dáwọ́ ìjà dúró la sí àgọ́ wọn.Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,gbogbo irin ẹnu ọ̀nà wọn ti di fífọ́.

31. Iránsẹ́ kan ń tẹ̀lé òmírànláti sọ fún Ọba Bábílónì pégbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.

32. Odò tí ó ṣàn kọjá kò ṣàn mọ́ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33. Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ nìyìí:“Ọmọbìnrin Bábílónì dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34. “Nebukadinésárì Ọba Bábílónì tó jẹ wá run,ó ti mú kí ìdààmú bá wa,ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,lẹ́yìn náà ni “Ó pọ̀ wá jáde.

35. Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe síẹran ara wa wà lórí Bábílónì;”èyí tí àwọn ibùgbé Síónì wí.“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogboàwọn tí ń gbé Bábílónì,”ni Jérúsálẹ́mù wí.

36. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lóríohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,èmi yóò mú kí omi òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.

Jeremáyà 51