Jeremáyà 51:26-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. A kò ní mú òkúta kankan látiọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbífún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò diahoro títí ayé,”ní Olúwa wí.

27. “Gbé àṣíá sókè ní ilẹ̀ náà, fọnipe láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!Pèṣè àwọn orílẹ̀ èdè sílẹ̀ láti bá jagun,pe àwọn ìjọba yìí láti doju kọ ọ́,Árárátì, Mínínì àti Ásíkẹ́nì.Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,rán àwọn ẹṣin síi bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28. Pèsè àwọn orílẹ̀ èdè láti bá jagun,àwọn Ọba Médíà, Gómìnà àti gbogboọmọ ìgbìmọ̀ wọn àti gbogbo orílẹ̀ èdè tí wọ́n jọba lé lórí.

29. Ilẹ̀ wárìrì síhìn ín sọ́hùn ún, nítorí péète Olúwa, sí Bábílónì dúróláti ba ilẹ̀ Bábílónì jẹ́ lọ́nàtí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.

30. Gbogbo àwọn jagunjagunBábílónì tó dáwọ́ ìjà dúró la sí àgọ́ wọn.Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,gbogbo irin ẹnu ọ̀nà wọn ti di fífọ́.

31. Iránsẹ́ kan ń tẹ̀lé òmírànláti sọ fún Ọba Bábílónì pégbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.

Jeremáyà 51