Jeremáyà 48:40-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Móábù.

41. Koríko kan yóò di kíkóàti àwọn ìlú olódì.Ní ọjọ́ náà ọkàn akọni Móábùyóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.

42. A ó pa Móábù run gẹ́gẹ́ bíorílẹ̀ èdè nítorípé ó gbéraga sí Olúwa.

43. Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídèń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Móábù,”ní Olúwa wí.

44. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fúnẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìnẹnikẹ́ni tí o bá jáde sítanínú ọ̀fìn ní à ó múnínú okùn dídè nítorí tíèmi yóò mú wá sóríMóábù àní ọdún Ìjìyà rẹ,”ní Olúwa wí.

45. “Ní abẹ́ òjìji Hésíbónìàwọn tí ó sá dúró láìníolùrànlọ́wọ́ nítorí iná ti jáde wáláti Hésíbónì àti ọwọ́ ináláti àárin Síónì sì jó iwájú orí Móábù runàti agbárí àwọn ọmọ àlùfáà.

46. Ègbé ní fún ọ Móábù!Wọn yóò sì kó àwọn ọmọkùnrin yín lọ síilẹ̀ àjèjì àti àwọn ọmọbìnrin yín lọ sí ìgbékùn.

Jeremáyà 48