Jeremáyà 46:16-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Wọn yóò máa ṣubú léralérawọn yóò máa ṣubú lu ara wọn.Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padàsí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa,kúrò níbi idà àwọn aninilára.’

17. Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé,‘Ariwo lásán ni Fáráò Ọba Éjíbítì pa,ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’

18. “Bí èmi ti wà láàyè,” ni Ọba,ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ ogun wí pé,“nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tábórì láàrin àwọn òkè àtigẹ́gẹ́ bi Kámẹ́lì lẹ́bàá òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.

19. Iwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Éjíbítì pèsèohun èlò ìrìn-àjò fún ara rẹnítorí Nófù yóò di ahoro a ó sì fi jóná,láìní olùgbé.

20. “Ẹgbọ̀rọ̀ abo màlúù tó lẹ́wà ní Éjíbítìṣùgbọ́n eṣinṣintí yóò le ń bọ̀ láti àríwá.

21. Àwọn jagunjagun rẹ̀dàbí àbọ́pa màlúù.Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà,wọn ó sì jùmọ̀ sá,wọn kò ní le dúró,Nítorí tí ọjọ́ ibi ńbọ̀ lórí wọnàsìkò láti jẹ wọ́n níyà.

22. Éjíbítì yóò pòṣé bí ejò tí ń sábí ọmọ ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára.Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké,gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.

23. Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,”ni Olúwa wí,“nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀,nítorí pé wọ́n pọ̀ ju elẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.

24. A ó dójú ti ọmọbìnrin Éjíbítì,a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”

25. Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ, Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí pé: “Èmi ṣetán láti fi ìyà jẹ Ámónì, òrìṣà Tíbísì, Fáráò Éjíbítì àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti àwọn Ọba rẹ̀ àti àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Fáráò.

26. Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadinésárì Ọba Bábílónì, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Éjíbítì yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.

27. “Má bẹ̀rù, ìwọ Jákọ́bù ìránṣẹ́ mi,má fòyà, ìwọ Ísírẹ́lì.Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jínjìn,àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn.Jákọ́bù yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò,kò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rù bà á.

Jeremáyà 46