Jeremáyà 41:3-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Íṣímáẹ́lì sì tún pa gbogbo àwọn Júù tí wọ́n wà pẹ̀lú Jedaláyà ní Mísípà, àti gbogbo àwọn ọmọ ogun Bábílónì tí wọ́n wà níbẹ̀ bákan náà.

4. Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Jedaláyà kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀

5. Àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣékémù, Ṣílò àti Saaríà, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n sá ara wọn lọ́gbẹ́ wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.

6. Ísímáẹ́lì ọmọkùnrin Nétanáyà jáde kúrò láti Mísípà láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sunkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹwá sọ́dọ̀ Jedaláyà ọmọkùnrin Álíkámù.”

7. Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Ísímáẹ́lì ọmọkùnrin Nètanáyà àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ìhò kan.

Jeremáyà 41