Jẹ́nẹ́sísì 46:18-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jákọ́bù bí nípaṣẹ̀ Ṣílípà, ẹni tí Lábánì fi fún Líà ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún (16) lápapọ̀.

19. Àwọn ọmọkùnrin Rákélì aya Jákọ́bù:Jósẹ́fù àti Bẹ́ńjámínì.

20. Ní Éjíbiti, Áṣénátù ọmọbìnrin Pọ́tíférà, alábojútó àti àlùfáà Ónì, bí Mánásè àti Éfúráímù fún Jósẹ́fù.

21. Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì:Bélà, Békérì, Áṣíbélì, Gérà, Náámánì, Éhì, Rósì, Múpímù, Húpímù àti Árídà.

22. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rákẹ́lì bí fún Jákọ́bù. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

Jẹ́nẹ́sísì 46