6. Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yó'mọ, afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
7. Àwọn sìírì ọkà méje tí kò yó'mọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yó'mọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Fáráò jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
8. Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Éjíbítì. Fáráò rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtúmọ̀ àlá náà fún un.
9. Nígbà náà ni olórí agbọ́tí wí fún Fáráò pé, “Lónìí ni mo rántí àìṣedéédé mi.
10. Nígbà kan tí Fáráò bínú sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, tí ó sì fi èmi àti olórí alásè sínú ẹ̀wọn ní ilé olórí ẹ̀sọ́.
11. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa lá àlá, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.