Jẹ́nẹ́sísì 23:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ábúráhámù sì gba ohun tí Éfúróni wí, ó sì wọn iye owó fàdákà náà lójú gbogbo ènìyàn: irínwó owó idẹ fàdákà gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n oníṣòwò ayé ìgbà náà.

17. Báyìí ni ilẹ̀ Éfúrónì tí ó wà ni Mákípélà nítòòsí Mámúrè-ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,

18. bí ohun-ìní fún Ábúráhámù níwájú gbogbo ará Hétì tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.

19. Lẹ́yìn náà ni Ábúráhámù sin aya rẹ̀ Sárà sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Mákípélà nítòòsí Mámúrè (tí í ṣe Ébúrónì) ní ilẹ̀ Kénánì.

20. Ilẹ̀ náà àti ihò-àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hítì fi fún Ábúráhámù gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.

Jẹ́nẹ́sísì 23