Jẹ́nẹ́sísì 23:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ṣárà sì pé ọmọ ọdún mẹ́tà-dín-láàádóje (127)

2. ó sì kú ní Kíríátì-Áríbà (ìyẹn ní Hébúrónì) ní ilẹ̀ Kénánì, Ábúráhámù lọ láti sọ̀fọ̀ àti láti sunkún nítorí Ṣárà.

3. Ábúráhámù sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hítì wí pé,

4. “Iwo jẹ́ àjèjì àti àlejò láàrin yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”

5. Àwọn ará Hítì dá a lóhùn pé,

6. “Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrin wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dárajù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dùn ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”

Jẹ́nẹ́sísì 23