Ékísódù 15:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Olúwa ni agbára àti orin mi;òun ti di Olùgbàlà mi,òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín,Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.

3. Ologun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,

4. Kẹ̀kẹ́-ogun Fáráò àti ogun rẹ̀ni ó mú wọ inú òkun.Àwọn ọmọ ogun Fáráò tó jáfáfá jùlọni ó rì sínú òkun pupa.

5. Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀;Wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.

6. “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa,pọ̀ ní agbára.Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa,fọ́ àwọn ọ̀ta túútúú.

Ékísódù 15