19. Nǹkan kékeré ni èyí sáà jásí lójú rẹ, Olúwa Ọlọ́run; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí há ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Ọlọ́run?
20. “Àti kín ní ó tún kù tí Dáfídì ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Ọlọ́run mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21. Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22. “Ìwọ sì tóbi, Olúwa Ọlọ́run: kò sì sí ẹni tí ó dà bí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.