2 Sámúẹ́lì 3:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ogun náà sì pẹ́ títí láàrin ìdílé Ṣọ́ọ̀lù àti ìdílé Dáfídì: agbára Dáfídì sì ń pọ̀ si i, ṣùgbọ́n ìdílé Ṣọ́ọ̀lù ń rẹ̀yìn si i.

2. Dáfídì sì bí ọmọkùnrin ní Hébírónì: Ámónì ni àkọ́bí rẹ̀ tí Áhínóámù ará Jésírẹ́lì bí fún un.

3. Èkéjì rẹ̀ sì ni Kíléábù, tí Ábígáílì àya Nábálì ará Kárímẹ́lì;bí fún un ẹ̀kẹta sì ni Ábúsálómù ọmọ tí Máákà ọmọbìnrin Tálímáì ọba Gésúrì bí fún un.

4. Ẹ̀kẹ́rin sì ni Àdóníjà ọmọ Hágítì;àti ìkarún ni Séfátíà ọmọ Ábítalì;

5. Ẹ̀kẹfà sì ni Ítíréámù, tí Égílà àya Dáfídì bí fún un.Wọ̀nyí ni a bí fún Dáfídì ni Hébúrónì.

6. Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàárin ìdílé Ṣọ́ọ̀lù àti ìdílé Dáfídì, Ábínérì sì dì alágbára ní ìdílé Ṣọ́ọ̀lù.

2 Sámúẹ́lì 3