3. Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
4. Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Ábúsálómù, àti lójú gbogbo àwọn àgbà Ísírẹ́lì.
5. Ábúsálómù sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Húṣáì ará Áríkì, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
6. Húṣáì sì dé ọ̀dọ̀ Ábúsálómù, Ábúsálómù sì wí fún un pé, “Báyìí ni Áhítófélì wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”