2 Sámúẹ́lì 14:28-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ábúsálómù sì gbé ni ọdún méjì ní Jérúsálẹ́mù kò sì rí ojú ọba.

29. Ábúsálómù sì ránṣẹ́ sí Jóábù, láti rán an sí ọba: ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.

30. Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Jóábù gbé ti èmi, ó sì ní ọkà níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì tinábọ̀ ọ́.” Àwọn ìrànṣẹ́ Ábúsálómù sì tinábọ oko náà.

31. Jóábù sì dìde, ó sì tọ Ábúsálómù wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tinábọ oko mi?”

32. Ábúsálómù sì dá Jóábù lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Géṣúrì wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn-ún ṣíbẹ̀!” ’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”

33. Jóábù sì tọ ọba wá, ó sì rò fún un: ó sì ránṣẹ́ pe Ábúsálómù, òun sì wá sọ́dọ̀ ọba, ó tẹríba fún un, ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀ níwájú ọba, ọba sì fi ẹnu ko Ábúsálómù lẹ́nu.

2 Sámúẹ́lì 14