2 Sámúẹ́lì 10:10-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Ábíṣáì àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ámónì.

11. Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Síríà bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́: ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ámónì bá sì pọ̀ jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.

12. Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”

13. Jóábù àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Síríà pàdé ìjà: wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.

14. Nígbà tí àwọn ọmọ Ámónì sì ríi pé àwọn ará Síríà sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Ábíṣáì, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Jóábù sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ámónì, ó sì wá sí Jérúsálẹ́mù.

15. Nígbà tí àwọn ará Síríà sì ríi pé Àwọn ṣubú níwájú Ísírẹ́lì: wọ́n sì kó ara wọn jọ

16. Hadadésérì sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Síríà tí ó wà ní òkè odò jáde wá: wọ́n sì wá sí Hélámì; Sóbákì olórí ogun Hedareṣérì sì ṣe olórí wọn.

2 Sámúẹ́lì 10