1 Sámúẹ́lì 2:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Hánà sì gbàdúrà pé:“Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa;Ìwọ agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa.Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀ta mi,nítorí ti èmi yọ̀ ni igbala rẹ̀

2. “Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa;kò sí ẹlòmíràn bí kò se ìwọ;kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.

3. “Má ṣe halẹ̀;má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jádenítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa,láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.

4. “Ọrun àwọn alágbára ti ṣẹ́,àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.

5. Àwọn tí ó yọ̀ fún òunjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe,àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní: tóbẹ́ẹ̀ ti àgàn fi bí méje.Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.

6. “Olúwa pa ó sì sọ di ààyè;ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà-òkú, ó sì gbé dìde.

1 Sámúẹ́lì 2