29. Bílà, Ésémù, Tóládì,
30. Bétúélì, Hórímà, Síkílágì,
31. Bẹti máríkóbótì Hórímà; Hásárì Ṣúsímù, Bẹti Bírì àti Ṣáráímì. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dáfídì,
32. agbégbé ìlú wọn ni Étamù Háínì, Rímónì, Tókénì, Áṣánì àwọn ìlú márùnún
33. Àti gbogbo ìletò tí ó wà ní agbégbé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti dé Bálì Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn, wọ́n sì pa ìwé ìtàn ìdílé mọ́.
34. Méṣóbábù Jámilékì, Jóṣáì ọmọ Ámásáyà,
35. Jóẹ́lì, Jéhù ọmọ Jósíbíà, ọmọ Ṣéráíáyà, ọmọ Ásíẹ́lì,
36. Àti pẹ̀lú Élíóénáì, Jákóbà, Jéṣóháiyá, Ásáíyà, Ádíélì, Jésímíẹ́lì, Bénáíyà,
37. Àti Ṣísà ọmọ ṣífì ọmọ Álónì, ọmọ Jédáíyà, ọmọ Ṣímírì ọmọ Ṣémáíyà.
38. Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ síi gidigidi,
39. Wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gédórì. Lọ títí dé ìlà òrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn
40. Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ará Ámù ni ó ń gbé bẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.