23. Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò bàbá a Rẹ̀ Dáfídì. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Ísírẹ́lì sì gbọ́ràn sí i lẹ́nu.
24. Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dáfídì tẹrí ara wọn ba fún ọba Sólómónì.
25. Olúwa gbé Solómónì ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Ísírẹ́lì, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọlá ńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú Rẹ̀ tí ó jẹ lórí Ísírẹ́lì.
26. Dáfídì ọmọ Jéṣè jẹ́ ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì.
27. Ó jọba lórí Ísírẹ́lì fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jọba ní Hẹ́súrónì, ó sì jọba ní ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n (33) ní Jérúsálẹ́mù.
28. Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Sólómónì ọmọ Rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀
29. Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dáfídì, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwe ìrántí ti Sámúẹ́lì aríran, ìwé ìrántí ti Nátanì wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gádì aríran,
30. lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára Rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí Rẹ̀, àti lórí Ísírẹ́lì, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.