Sáàmù 9:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ìwọ ti bá orílẹ̀ èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6. Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀ta,Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;Àní ìrántí wọn sì ti sègbé.

7. Olúwa jọba títí láé;ó ti gbé ìtẹ́ Rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

8. Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ àyé ní òdodo;yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9. Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10. Àwọn tí ó mọ orúkọ Rẹ yóò gbà ọ́ gbọ́,èmi tàbí ìwọ, Olúwa, kò kọ àwọn to ń wa a sílẹ̀.

Sáàmù 9