Sáàmù 7:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.

9. Ọlọ́run Olódodo,Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburútí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.

10. Aṣà mi ní Ọlọ́run tí ó gajù,ẹni tí ń dáàbò bo àwọn ẹni gíga nípa ti èmi.

11. Ọlọ́run ni onídàájọ́ tòótọ́,Ọlọ́run tí ń sọ ìrúnú Rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.

12. Bí kò bá yípadà,òun yóò pọ́n idà Rẹ̀ múó ti fa ọrun Rẹ̀ le náó ti múra Rẹ̀ sílẹ̀

13. Ó ti pèṣè ohun ìjà ikú sílẹ̀;ó ti pèṣè ọfà iná sílẹ̀.

14. Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,tí ó sì lóyùn wàhálà ó bí èké jáde.

15. Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jádejìn sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.

16. Wàhálà tí ó fà padà sórí Rẹ̀;Ìwà ipá Rẹ̀ padà sórí ara Rẹ̀.

17. Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo Rẹ̀Èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa tí ó ga jùlọ.

Sáàmù 7