Sáàmù 46:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára waó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ nínú ìgbà ìpọ́njú.

2. Nítori náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ sí ayé ní ìdítí òkè sì ṣubú sínú òkun

3. Tí omi Rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mìtí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára Rẹ̀. Sela

4. Odò ńlá kan wà tí sísàn Rẹ̀ mú ìnú ìlú Ọlọ́run dùnibi mímọ́, nibi ti ọ̀gá ògo ń gbé.

5. Ọlọ́run wà pẹ̀lú Rẹ̀, kò ní yẹ̀:Ọlọ́run yóò ràn an lọ́wọ́ ní kùtùkùtù ọ̀wúrọ̀

6. Àwọn orílẹ̀ èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba subúó gbé ohun Rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.

7. Ọlọ́run awọn ọmọ ogún wà pẹ̀lú waỌlọ́run Jákọ́bù ni ààbò wa

8. Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwairú ahoro tí ó ṣe ní ayé

Sáàmù 46