Sáàmù 45:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Gbogbo aṣọ Rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjíá àti alóe àti kaṣíà;láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣeorin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú Rẹ̀ dùn.

9. Àwọn ọmọbìnrin àwọn aládé wànínú àwọn àyànfẹ́ Rẹ̀ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúrónínú wúrà ófórì.

10. Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí Rẹ̀ símigbàgbé àwọn ènìyàn Rẹ àti ilé baba Rẹ

11. Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà Rẹ gidigidinítorí òun ni Olúwa Rẹkí ìwọ sì máa tẹríba fún un.

12. Ọmọbìnrin ọba tirẹ̀ yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùnàwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojú rere Rẹ̀.

13. Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárin ilé Rẹ̀aṣọ ìbalẹ̀ Rẹ̀ a ṣe é lọ́sọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà

14. Nínú aṣọ ìbànújẹ́ iyebíye ni a mú-un wá sí ọ̀dọ̀ ọbaàwọn wúndíá ẹgbẹ́ Rẹ̀ tẹ̀ lé e wọ́n, sí mú-un tọ̀ ọ́ wá

15. Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùnwọ́n sì wọ ààfin ọba.

Sáàmù 45