Sáàmù 42:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Bí àgbọ̀nrín tí ń mí hẹlẹ sí ìpa odò omi,bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi n mì hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run

2. Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?

3. Oúnjẹ mi ní omijé miní ọ̀sán àti ní òru,nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́,“Ọlọ́run Rẹ̀ dà?”

4. Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́runpẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.

5. Èéṣe tí o fi n rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?Èéṣe tí ara Rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?Ìwọ ṣe ìrètí ni ti Ọlọ́run,nítorí èmi yóò sáà máa yìn ín.

Sáàmù 42