Sáàmù 10:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èé ha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?È ha ti ṣe tí ìwọ fi ara Rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2. Nínú àrékérekè ènìyàn búburú ti ó gbérò ni kí a ti mú wọn,lí a mú-un nínú ìlànà tí o gbérò.

3. Ó ń fọ́nnu nínú ìfẹ́ inú ọkàn Rẹ̀;o bùkún olójúkòkòrò ó sì ń kẹ́gàn Olúwa

4. Ènìyàn búburú kò lè rí i nínú ìgbéraga Rẹ̀;kò sí àyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò Rẹ̀;

Sáàmù 10