Òwe 3:28-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,“Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; ó fún ọ lọ́lá”nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.

29. Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.

30. Má ṣe fẹ̀ṣùn kan ènìyàn láì-ní-ìdínígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31. Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgantàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀,

32. Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyìídáyidàṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.

33. Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo

34. Ó fi àwọn oníyẹ̀yẹ́ ṣe yẹ̀yẹ́Ṣùgbọ́n ó fi oore ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀

35. ọlọ́gbọ́n jogún iyìṢùgbọ́n àwọn aláìgbọ́n ni ó dójú tì.

Òwe 3