Òwe 3:11-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwamá si ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12. Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wíbí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,ẹni tí ó tún ní òye síi

14. Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.

15. Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;kò sí ohunkohun tí a lè fi wé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.

16. Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;ní ọwọ́ òsì rẹ̀ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.

17. Àwọn ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà ìtura,òpópónà rẹ̀ sì jẹ́ ti àlàáfíà.

18. Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbàá;àwọn tí ó bá sì dìí mú yóò rí ìbùkún gbà.

19. Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipòo wọn;

20. Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní ìyà,àwọ̀sánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21. Ọmọ mi pa ìdájọ́ tí ó yè kooro mọ́ àti ìmọ̀yàtọ̀,má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn

22. wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọàti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ

23. Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìṣéwu,ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀;

Òwe 3