Òwe 21:22-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,ó sì bi ibi-gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.

23. Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.

24. Agbéraga àti alágídí ènìyàan ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,tí ń hùwà nínú àdábọwọ́ ìgbéraga.

25. Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.

26. Ó ń fi ìlara ṣojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.

27. Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:mélòómélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà-ibi?

Òwe 21