Òwe 21:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburúó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

13. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,òun tìkárarẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14. Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:àti owó-àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,dẹ́kun ìbínú líle.

15. Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

16. Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.

17. Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di talákà:ẹni tí ó fẹ́ ọtí-wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.

18. Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó-ìràpadà fún olódodo,àti olùrékọjá fún ẹni dídúró-ṣinṣin.

Òwe 21