Òwe 2:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. bí ìwọ bá wá ṣàfẹ́rì rẹ̀ bí i fàdákàtí o sì wa kiri bí i fún ohun iyebíye tó fara sin.

5. Nígbà náà ni òye ẹ̀rù Olúwa yóò yé ọ,tí ó sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.

6. Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá

7. Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,Òun ni aṣà fún àwọn tí ń rìn déédé,

8. ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

9. Nígbà náà ni òye ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì dára,tí ó dára yóò yẹ́ ọ—gbogbo ọ̀nà dídara.

Òwe 2