1. Nígbà tí Sáńbálátì, Tòbáyà Géṣémù ará Árábíà àti àwọn ọ̀taa wa tó kù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́ kù nínú un rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì rì àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2. Ṣáńbálátì àti Géṣémù rán iṣẹ́ yìí sí mi pé: “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ónò.”Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbérò láti ṣe mí ní ibi;
3. Bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé; “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4. Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5. Ní ìgbà kárùn-ún, Sáńbálátì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú apo ìwé wà ní ọwọ́ọ rẹ̀
6. tí a kọ sínú un rẹ̀ pé:“A ròyìn rẹ láàárin àwọn orílẹ̀ èdè—Géṣémù sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé—ìwọ àti àwọn Júù ń gbérò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbérò láti di ọba wọn
7. àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù: ‘ọba kan wà ní Júdà!’ Nísinsìn yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”