Lúùkù 11:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Mo wí fún yín, bí òun kò tilẹ̀ ti fẹ́ dìde kí ó fifún un nítorí tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n nítorí àwíìyánu rẹ̀, yóò dìde, yóò sì fún un pọ̀ tó bí ó ti ń fẹ́.

9. “Èmí sì wí fún yín, Ẹ bèèrè, a ó sì fifún un yín; ẹ wá kiri, ẹ̀yin ó sì rí; ẹ kànkùn, a ó sì ṣí i sílẹ̀ fún yín.

10. Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá bèèrè, yóò rí gbà; ẹni tí ó sì ń wá kiri, yóò rí; àti ẹni tí ó kànkùn ni a ó ṣí i sílẹ̀ fún.

11. “Ta ni baba nínú yín tí ọmọ rẹ̀ yóò bèèrè (àkàrà lọ́dọ̀ rẹ̀, tí yóò fún un ní òkúta? Tàbí bí ó bèèrè) ẹja, tí yóò fún un ní ejò dípò ẹja?

Lúùkù 11