Jóṣúà 3:12-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ǹjẹ́ nísinsìn yí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá (12) nínú àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.

13. Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹṣẹ̀ bọ odò Jọ́dánì, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbájọ bí òkítì kan.”

14. Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jọ́dánì, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.

15. Odò Jọ́dánì sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jọ́dánì, tí ẹṣẹ̀ wọn sì kan etí omi,

16. omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbájọ bí òkítì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Ádámù, tí ó wà ní tòsí Sárétanì; nígbà tí omi tí ń ṣàn lọ sínú òkun aginjù, (Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátapáta. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdì kejì ní ìdojúkọ Jẹ́ríkò.

17. Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárin Jọ́dánì, nígbà tí gbógbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀ èdè náà fi ré kọjá nínú odò Jọ́dánì lórí ilẹ̀ gbígbẹ.

Jóṣúà 3