Jóòbù 1:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Sì kíyèsí i, ẹfúfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọ lu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọdọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.

20. Nígbà náà ni Jóòbù dìde, ó sì fa aṣọ ìgunwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà

21. wí pé:“Ní ìhòòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá,ni ìhòòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ síbẹ̀. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ,ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”

22. Nínú gbogbo èyí Jóòbù kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.

Jóòbù 1