Jòhánù 1:41-45 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. Ohun àkọ́kọ́ tí Ańdérù ṣe ni láti wá Símónì arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Mèṣáyà” (ẹni tí ṣe Kírísítì).

42. Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jésù.Jésù sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Símónì ọmọ Jónà: Kéfà ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Pétérù).

43. Ní ọjọ́ kéjì Jésù ń fẹ́ jáde lọ sí Gálílì, ó sì rí Fílípì, ó sì wí fún un pé, “Má a tọ̀ mí lẹ́yìn.”

44. Fílípì gẹ́gẹ́ bí i Ańdérù àti Pétérù, jẹ́ ará ìlú Bẹtiṣáídà.

45. Fílípì rí Nàtaníẹ́lì, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mósè kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀—Jésù ti Násárẹ́tì, ọmọ Jósẹ́fù.”

Jòhánù 1