Jeremáyà 37:9-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. “Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Bábílónì yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú;’ wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.

10. Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ ogun Bábílónì tí ń gbógun tì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”

11. Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ ogun Bábílónì ti kúrò ní Jérúsálẹ́mù nítorí àwọn ọmọ ogun Fáráò.

12. Jeremáyà múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Bẹ́ńjámínì láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrin àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.

Jeremáyà 37