Jẹ́nẹ́sísì 3:18-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èsùsú fún ọ,ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.

19. Nínú òógùn ojú rẹni ìwọ yóò máa jẹuntítí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀,nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá;erùpẹ̀ ilẹ̀ ṣáà ni ìwọ,ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”

20. Ádámù sì sọ aya rẹ̀ ní Éfà nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.

21. Olúwa sì dá ẹ̀wù awọ fún Ádámù àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n.

22. Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èṣo igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láàyè títí láéláé.”

23. Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Édẹ́nì láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá.

24. Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tan, ó fi àwọn Kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ̀nà ṣíwájú àti sẹ́yìn, sọ́ ọ̀nà tí ó lọ síbi igi ìyè, ní ìhà ìlà oòrún ọgbà Édẹ́nì.

Jẹ́nẹ́sísì 3