Jẹ́nẹ́sísì 24:59-63 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

59. Wọ́n sì gbà kí Rèbékà àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Ábúráhámù àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ má a lọ.

60. Wọ́n sì súré fún Rèbékà, wọn sì wí fun un pé,“Arábìnrin wa, ìwọ yóò di ìyáẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún.Ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹkí ó gba ibodè ọ̀ta a wọn.”

61. Nígbà náà ni Rèbékà àti àwọn ìránṣẹ́-bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ràkunmí, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rèbékà ó sì bá tirẹ̀ lọ.

62. Ísáákì sì ń ti Bia-Lahai-Róì bọ, nítorí ìhà gúsù ni ó ń gbé.

63. Ísáákì sáà jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àsàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ràkunmí tí ń bọ̀ wá.

Jẹ́nẹ́sísì 24